Home / Art / Àṣà Oòduà / E̩ Fi Àdúrà Rànmí Lọ́wọ́, Nítorí Ọmọkùnrin Mi Ti Lùgbàdi Àrùn Coronavirus … Igbákejì Ààrẹ Orílẹ̀ Yìí Nígbà Kan
Atiku

E̩ Fi Àdúrà Rànmí Lọ́wọ́, Nítorí Ọmọkùnrin Mi Ti Lùgbàdi Àrùn Coronavirus … Igbákejì Ààrẹ Orílẹ̀ Yìí Nígbà Kan

Ẹ fi àdúrà rànmí lọ́wọ́, nítorí ọmọkùnrin mi ti lùgbàdi àrùn coronavirus … igbákejì Ààrẹ Orílẹ̀ yìí nígbà kan

Fẹ́mi Akínṣọlá

Àjàkálẹ̀ àrùn kan tí gbogbo àgbáláayé ń kó bẹ́ẹ́rẹ́ fún lásìkò yìí tí kò mojú Ọba tìjòyè mẹ̀kúnù àti olówó ló tí kọlu ọmọ ìgbákejì Ààrẹ Orílẹ̀ yìí tẹlẹ o .
Olùdíje fún ipò Ààrẹ fẹ́gbẹ́ òṣèlú PDP, Atiku Abuabakar ló fọ̀rọ̀ yìí léde lójú òpó Twitter rẹ̀ lálẹ́ ọjọ́ Àìkú.

Atiku ṣàlàyé pé òun ti sọ fún àjọ tó ń gbógun ti àjàkálẹ̀ àrùn ní Nàìjíríà, NCDC, àti pé ọmọ náà ti ń gba ìtọ́jú nílé ìwòsàn olùkọ́ni Fásitì Abuja tó wà ní Gwagwalada.

”Inú mi yóó dùn tí ẹ bá le fi ọmọ mi sínú àdúrà yín, kí oníkálùkù rọra máa ṣe nítorí òtítọ́ ni pé àrùn coronavirus wà níta,” Atiku ló sọ bẹ́ẹ̀.

Atiku tún gbóríyìn fáwọn òṣìṣẹ́ ilé ìwòsàn káàkiri orílẹ̀-èdè Nàìjíríà fún iṣẹ́ takuntakun tí wọ́n ń ṣe lásìkò àjàkálẹ̀ àrùn covid-19 yìí.

”Mo rọ gbogbo ọmọ Nàìjíríà pé kí wọ́n má mi kàn tí a ó fi ṣẹ́gun àrùn coronavirus ní Nàìjíríà,” Atiku ló wòye bẹ́ẹ̀.

Ọgbọ̀n èèyàn làjọ NCDC ti kéde pé wọ́n tí ní àrùn afopin sí mímí èémí tí wọ́n ń pé ní coronavirus ní orílẹ̀ yìí, nínú èyí tí àwọn méjì ti rí ìwòsàn.

About ayangalu

One comment

  1. Sheikh of Igboland (King Ob????

    One of my oldest twitter friend omo odua!

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

Atiku-and-Tinubu

Atiku To Tinubu: How Did You Inherit Properties If You Are From Poor Background?

Atiku Abubakar, Presidential Candidate of the Peoples Democratic Party (PDP), has asked Asiwaju Bola Tinubu, his All Progressives Congress (APC) rival, to come clean on his source of wealth. During an interview with BBC Focus on Africa, on Tuesday, Tinubu said he “inherited” real estate which contributed to his wealth. The former governor of Lagos also likened himself to the United States billionaire, Warren Buffet. “Are they enemies of wealth, if they are not enemies of wealth–investments do yield. I ...