Home / Art / Àṣà Oòduà / Ganduje ti rọ Emir ìlúu Kánò, Sanusi Lamido Sanusi lóyè
Abdullahi Ganduje governor of Kano
Abdullahi Ganduje, Governor of Kano

Ganduje ti rọ Emir ìlúu Kánò, Sanusi Lamido Sanusi lóyè

Ganduje ti rọ Emir ìlúu Kánò, Sanusi Lamido Sanusi lóyè

Ìdààmú ilé ọlá kan kìí rọ̀, ko ko ko níí le. Ní báyìí Ìgbìmọ̀ ìsàkóso Ìjọba ìpínlẹ̀ Kano ti rọ Emir Sanusi lóyè ní ọjọ́ Ajé, ọjọ́ kẹsàn án Oṣù kẹta ọdún 2020.

. Ó ti tó ọjọ́ mẹ́ta kan tí gbún-gbùn-gbún ti ń wáyé láàrin gómìnà ìpínlẹ̀ Kano, Abdullahi Umar Ganduje àti Ẹmia Lamido Sanusi.

Akọ̀wé Ìjọba ìpínlẹ̀ Kano nínú àtẹ̀jáde kan ṣàlàyé pé ìgbìmọ̀ ìṣèjọba ìpínlẹ̀ náà yọ ọ́ lóyè lórí ẹ̀sùn pé ó ń tako àṣẹ tí gómìnà ìpínlẹ̀ náà ń pa.

Bákan náà ló ní lára àwọn ìwà títàpá sófin àti àṣẹ náà ni bí ó ṣe kọ láti farahàn láwọn ìpàdé àti ètò tí Ìjọba ìpínlẹ̀ náà bá gbé kalẹ̀ láìsí àwíjàre tó yanrantí.

Ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà ni Mallam Sanusi ti tako àwọn àgbékalẹ̀ òfin tó de oyè jíjẹ ní ìpínlẹ̀ náà eléyìí tó ní yóó ba iyì ìlú Kano jẹ́ bí wọn kò bá mójútó o.

Ìjọba ìpínlẹ̀ Kano ní àwọn gbé ìgbésẹ̀ láti yọ Sanusi nípò Ẹmia ìlú Kano láti dáàbò bo àṣà, ìṣẹ̀ṣe àti ẹ̀sìn tí ó mú iyì bá ìlú Kano.

Gómìnà Ganduje ti ìpínlẹ̀ Kano wá ké sí àwọn èèyàn Ìpínlẹ̀ náà láti fọkànbalẹ̀ kí wọ́n sì máa bá iṣẹ́ òòjọ́ wọn lọ àti pé láìpẹ́ ni wọn yóó yan Ẹmia tuntun.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED FOOL in Your ancestral Land.

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED Harlequin in Your ancestral Land.

The quote for today is a page from Toyin Falola’s book, ‘Yoruba Warlords of the 19th Century’. To a lot of Yoruba Muslims. Islam means servitude to Usman Dan Fodio’s estate at Sokoto. They indulge in the same idiocy that led to the fall of the great Hausa civilization. Many Yoruba Muslims from Oyo are a dangerously brainwashed set of people that would pose future danger for the preservation of Yorubaland like their ancestors who pledged allegiance to Ilorin and ...