Home / Art / Àṣà Oòduà / Ìjọba àpapọ̀ f’ẹ́ já iná mànàmáná orílẹ̀èdè Togo àti Benin Republic nítorí gbèsè $7m
Phcn nepa

Ìjọba àpapọ̀ f’ẹ́ já iná mànàmáná orílẹ̀èdè Togo àti Benin Republic nítorí gbèsè $7m

Ìjọba àpapọ̀ f’ẹ́ já iná mànàmáná orílẹ̀èdè Togo àti Benin Republic nítorí gbèsè $7m

Ariwo t’íjọba àpapọ̀ Nàìjíríà ń pa lé àwọn tó jẹ ẹ́ ni gbèsè owó iná nìyí báyìí o.

Ṣùgbọ́n lọ́tẹ̀ yìí kìí ṣe àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà nìjọba àpapọ̀ ń bá wí, bíkòṣe àwọn Ìjọba orílẹ̀-èdè méjì kan lẹ́kùn ìwọ̀ oòrùn ilẹ̀ Áfírìkà.

Bẹ́ẹ̀ ni, Ìjọba àpapọ̀ Nàìjíríà ti jáwé ìkìlọ̀ ránṣẹ́ s’órílẹ̀èdè Togo àti Benin Republic pé kí Ìjọba ibẹ̀ tètè san gbèsè iná ẹ̀lẹ́ńtírìkì tí wọ́n jẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.

Hmmm… Alága àjọ àpapọ̀ iná mànamáná lẹ́kùn ìwọ oòrùn ilẹ̀ Afirika, Usman Gur Mohammed ni orílẹ̀-èdè méjéèjì yí jẹ Nàìjíríà lówó iná tó tó mílíọ̀nù méje dọ́là owó ilẹ̀ Amẹ́ríkà, ($7m).

Ọ̀gbẹ́ni Miohammed ní òun ò le joyè akótilétà tí yóó máa yan àwọn ọmọ Nàìjíríà jẹ lórí ọ̀rọ̀ iná ọba.

Gẹ́gẹ́ bí ó ṣe sọ, ‘Ọgọ́rùn mílíọ̀nù dọ́là owó ilẹ̀ Amẹ́ríkà, ($100m) ni orílẹ̀-èdè Benin àti Togo ń jẹ ní gbèsè owó iná nígbà tí mo dé ipò Alága àjọ apínná ọba Nàìjíríà, TCN. Ní báyìí mo ti gba owó náà ku mílíọ̀nù méje dọ́là owó ilẹ̀ Amẹ́ríkà, ($7m).”

Owó iná tí orílẹ̀-èdè Niger republic ní tirẹ̀ ń jẹ dín díẹ̀ ní mílíọ̀nù méjì dọ́là owó ilẹ̀ Amẹ́ríkà, ($2m). A ò sì ní fi wọ́n sílẹ̀. A máa já iná wọn gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń já iná àwọn èèyàn ní Nàìjíríà níbí ni.”

Ó ní kò sójú àánú lọ́rọ̀ iná ọba lílò àti pé, kò ní sí ààyè fún àwọn èèyàn láti máa lo iná ẹ̀lẹ́ńtírìkì orílẹ̀-èdè Nàìjíríà láì san owó rẹ̀.

Ní kété táwọn ọmọ Nàìjíríà gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, onírúurú èsì ni wọ́n ti ń fọ̀ lórí rẹ̀.

Àwọn ọmọ Nàìjíríà kan ń tara ni pé inú àwọn kò dùn sí Ìròyìn náà nítorí pé ó ní n tí ojú àwọn ọmọ Nàìjíríà tó jẹ owó díẹ̀ lásán ń rí lọ́wọ́ àwọn òṣìṣẹ́ amúnáwá eléyìí tó fihàn pé Ìjọba àpapọ̀ kìí ṣe irú rẹ̀ fún àwọn ilẹ̀ òkèèrè tó jẹ ẹ́ ní gbèsè owó iná.

Bákan náà láwọn kan kọminú pé orílẹ̀-èdè Nàìjíríà kò le è pèsè iná tó dúró déédé fún àwọn èèyàn rẹ̀ tó jẹ́ oníǹkan, ṣùgbọ́n ó leè máa pèsè iná ológeere fáwọn ti ilẹ̀ mìíràn tó sì jẹ́ pé lẹ́yìn ò rẹyìn wọn kò ní san owó iná náà.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED FOOL in Your ancestral Land.

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED Harlequin in Your ancestral Land.

The quote for today is a page from Toyin Falola’s book, ‘Yoruba Warlords of the 19th Century’. To a lot of Yoruba Muslims. Islam means servitude to Usman Dan Fodio’s estate at Sokoto. They indulge in the same idiocy that led to the fall of the great Hausa civilization. Many Yoruba Muslims from Oyo are a dangerously brainwashed set of people that would pose future danger for the preservation of Yorubaland like their ancestors who pledged allegiance to Ilorin and ...