Home / Art / Àṣà Oòduà / Ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn wọ́gilé ìyọnípò Oshiomole gẹ́gẹ́ bíi alága ẹgbẹ́ òṣèlú APC
ile ejo

Ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn wọ́gilé ìyọnípò Oshiomole gẹ́gẹ́ bíi alága ẹgbẹ́ òṣèlú APC

Ọ̀rọ̀ fini lògbòlògbò yini nù lọ̀rọ̀ ọ Alága gbogbo gbòò ẹgbẹ́ òsèlú APC dà báyìí o, bí Ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn ìlú Abuja ti ní Adams Oshiomhole sì ni Alága gbogbo gbòò fún ẹgbẹ́ òṣèlú APC.

Ìgbìmọ̀ ẹlẹ́ni mẹ́ta tó ń gbọ́ ẹjọ́ náà, tí adájọ́ Abubaka Datti Yahaya kó sòdí wọ́gilé ẹjọ́ tí ilé ẹjọ́ gíga ìlú Abuja dá Ṣaájú, léyìí tó yọ Oshiomole nípò gẹ́gẹ́ bí Alága ẹgbẹ́ ọ̀hún.

Ṣaájú ni oshiomole ti rọ ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn náà láti gbé ìdájọ́ ìyọnípò rẹ̀ náà tì ṣí ẹ̀gbẹ́ kan.

Nígbà tó ń gbé ìdájọ́ rẹ̀ kalẹ̀, adájọ́ náà kìlọ̀ fún àwọn tí ọ̀rọ̀ ọ̀hún kàn láti má gbé ìgbésẹ̀ tí yóó tako ìdájọ́ tó gbé kalẹ̀.

Lẹ́yìn náà ló rọ àwọn ẹgbẹ́ òṣèlú láti máa yanjú aáwọ̀ tó bá wà láàrin wọn gẹ́gẹ́ bí ọmọ ìyá dípò kí wọ́n máa yọ ilé ẹjọ́ lẹ́nu.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

nigerian police

Họ́wù! Àgọ́ ọlọ́pàá ni wọ́n tí fọmọ odó lu èèyàn méjì pa

Họ́wù! Àgọ́ ọlọ́pàá n wọ́n tí fọmọ odó lu èèyàn méjì pa Ará kò níí tán nílé alárà láé láé. À bí kínni kí á tí wí pẹ̀lú bí èèyàn méjì ti kú lẹ́yìn tí ọlọ́pàá kan fi ọmọ odó lu ọ̀dọ́ mẹ́ta fún pé wọ́n jí adìẹ. Ẹnìkẹta, Abdulwahab Bello, nìkan ni ó yè. Ṣùgbọ́n, ó fi ara gba ọgbẹ́, tí egungun rẹ̀ sì kán, lẹ́yìn tí ọlọ́pàá náà lù wọ́n ní àgọ́ ọlọ́pàá kan ní Ìpínlẹ̀ Bauchi. Abdulwahab ...