Home / Art / Àṣà Oòduà / Kùkùlajà Ètò Ààbò, Gani Adams Ní OPC Àtàwọn Míì Ṣetán Láti Ṣiṣẹ́ Pẹ̀lú Àwọn Òṣìṣẹ́ Elétò Ààbò Nílẹ̀ Oòduà (Yorùbá)
Aare Gani Adams

Kùkùlajà Ètò Ààbò, Gani Adams Ní OPC Àtàwọn Míì Ṣetán Láti Ṣiṣẹ́ Pẹ̀lú Àwọn Òṣìṣẹ́ Elétò Ààbò Nílẹ̀ Oòduà (Yorùbá)

Kùkùlajà ètò ààbò,Gani Adams ní OPC àtàwọn míì ṣetán láti ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn òṣìṣẹ́ elétò ààbò nílẹ̀ Oòduà (Yorùbá)
Fẹ́mi Akínṣọlá

Ṣé Oòduà (Yorùbá) bọ̀ wọ́n ní ọmọ onílùú kìí fẹ́ ò tú.
Gbogbo áwọn àgbààgbà nínú ẹgbẹ́ ajìjàgbara ẹgbẹ́ OPC àti Àgbẹ́kọ̀yà àtàwọn irú ẹgbẹ́ bẹ́ẹ̀ káàkiri ilẹ̀ Oòduà (Yorùbá) ní àwọn ti gbaradì báyìí láti ṣe ìrànlọ́wọ́ fáwọn òṣìṣẹ́ elétò ààbò káàkiri ilẹ̀ Oòduà (Yorùbá).
Ààrẹ Gani Adams tó jẹ́ olórí OPC tilẹ̀ sọ pé àṣẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn Gómìnà ìpínlẹ̀ Oòduà (Yorùbá) làwọn ń retí láti sètò ìgbésẹ̀ ètò ààbò tó mọ́yán lórí tí àwọn pe orúkọ rẹ́ ní Operation Àmọ̀tẹ́kùn”.

Àkànṣe ètò ààbò yìí ni ìròyìn sọ pé ó jẹ́ àjọmọ̀ àti àjọrò gbogbo Gómìnà ní ilẹ̀ Oòduà (Yorùbá) lójúnà àti pèsè ètò ààbò tó péye fún mùtú mùwà káàkiri ilẹ̀ náà.
Èrò àwọn Gómìnà yìí ló dá lórí bí ìjínigbé àti ìpànìyàn ṣe wọ́pọ̀ ní ẹkùn náà tí wọ́n sì gbèrò láti mú òpin débá ìwà burúkú bẹ́ẹ̀.
Ṣé ní nǹkan bíi oṣù Kẹwàá ọdún yìí ni wọ́n gbèrò láti kó ìmọ̀ náà jáde bí ọmọ tuntun.
Ààrẹ Gani Adams ṣàlàyé síwájú síi pé ”Operation Àmọ̀tẹ́kùn” wà láti ṣèkúnwọ́ fún àwọn àjọ ààbò káàkiri ilẹ̀ Oòduà (Yorùbá).
Àwọn àgbáríjọ ẹgbẹ́ tí wọ́n yóó lò ni ẹgbẹ́ OPC, Àgbẹ́kọ̀yà, Fijilanté, àtàwọn ẹgbẹ́ ọ̀dọ́ ilẹ̀ Oòduà (Yorùbá) àti ọlọ́de káàkiri ìletò.

Àwọn ẹgbẹ́ wọ̀nyí ti wá gbà láti ṣiṣẹ́ papọ̀ bẹ́ẹ̀ wọ́n ti kọ̀wé sí gbogbo Gómìnà, àtàwọn olórí elétò ààbò káàkiri ilẹ̀ Oòduà (Yorùbá).
Àgbáríjọpọ̀ àwọn ẹgbẹ́ yìí ni wọ́n tí ṣe púpọ̀ ìpàdé ní ìlú Eko tí wọn yóó sì tún ṣe ní ìlú Ibadan , tíí ṣe Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ní Ọjọ́rú ọ̀sẹ̀ yìí.

Ó ní kò sí bí ọ̀rọ̀ ètò ààbò yóó ṣe ṣeéṣe láì sí àwọn irinṣẹ́ ìbánisọ̀rọ̀ tó dájú. Ó ní àwọn ọkọ̀ ti wà, àwọn ọlọ́pàá sì ti wà nílẹ̀ àṣẹ àwọn Ọlọ́pàá ni wọ́n ń dúró dè.
Ó ní nígbà tí kò ti sí Ìpínlẹ̀ kan lórílẹ̀-èdè yìí tó ní àṣẹ láti ra ohun ìjà olóró, tó sì jẹ́ pé àwọn Gómìnà ti setán láti ṣe gbogbo ohun àmúyẹ láti ra ohun tó bá kù.

Ó wá ṣàlàyé pé, kò tíì sí àrídájú pé bóyá ọkọ̀ òfurufú kékeré yóó wà lára ohun tí wọ́n fẹ́ lò ṣùgbọ́n pé Ìjọba Ìpínlẹ̀ Ekiti ti ra ọkọ̀ bíi ogún sílẹ̀ fún ètò náà.
Alukoro fún Gómìnà Ìpínlẹ̀ Ogun, Kunle Somorin ṣàlàyé pé Gómìnà kọ̀ọ̀kan ni yóó kó ọkọ̀ ọgọ́rùn sílẹ̀ láti bẹ̀rẹ̀ ètò náà.

About ayangalu

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED FOOL in Your ancestral Land.

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED Harlequin in Your ancestral Land.

The quote for today is a page from Toyin Falola’s book, ‘Yoruba Warlords of the 19th Century’. To a lot of Yoruba Muslims. Islam means servitude to Usman Dan Fodio’s estate at Sokoto. They indulge in the same idiocy that led to the fall of the great Hausa civilization. Many Yoruba Muslims from Oyo are a dangerously brainwashed set of people that would pose future danger for the preservation of Yorubaland like their ancestors who pledged allegiance to Ilorin and ...