Home / Art / Àṣà Oòduà / Fìdáù Ajímọ̀bi, ẹbí nìkan ní wọ́n ń retí–Ẹbí Ajímọ̀bi
abiola ajimobi

Fìdáù Ajímọ̀bi, ẹbí nìkan ní wọ́n ń retí–Ẹbí Ajímọ̀bi

Fìdáù Ajímọ̀bi, ẹbí nìkan ní wọ́n ń retí–Ẹbí Ajímọ̀bi

Ṣé wọ́n ní kìí jẹ́ ti baba t’ọmọ, kó mọ́ ní ààlà. Èyí ló díá fún bí àwọn ẹbí olóògbé Abíọ́lá Ajímọ̀bi tí sàlàyé pé ,kí àwọn olùkẹ́dùn, ó má wulẹ̀ dààmu yọjú sí bi fìdáù, ní ìbámu pẹ̀lú n tí àjàkálẹ̀ àrùn apinni léèmí Kòrónáfairọ̀ọ̀sì n sọ , bí ó ti jẹ́ pé òní, ọjọ́ karùn-ún, oṣù Keje, ni àdúrà ọjọ́ kẹjọ yóó wáyé fún Gómìnà ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ tẹ́lẹ̀rí tó di olóògbé, Sẹ́nétọ̀ Isiaka Abíọ́lá Ajímọ̀bi.

Ètò àdúrà náà, Fìdáù, wà ní ìbámu pẹ̀lú àṣà àti ìṣẹ ẹ̀sìn Islam. Ìdílé olóògbé sọ nínú Ìkéde tó fi síta fún ètò àdúrà náà pé, ẹbí Ajímọ̀bi nìkan ni ètò àdúrà náà wà fún, nítorí òfin tó rọ̀ mọ́ ìtànkálẹ̀ àjàkálẹ̀ àrùn apinni léèmí Kòrónáfairọ̀ọ̀sì.

Ṣùgbọ́n ṣá, wọ́n ní àwọn aráàlú yóó ní àǹfààní láti wo bí ètò àdúrà náà bá ṣe ń lọ lórí amóhùnmáwòrán àti lórí ẹ̀rọ ayélujára.

Ọjọ́ kẹẹdọgbọn, oṣù Kẹfà, ọdún 2020, ni Abíọ́lá Ajímọ̀bi kú, síléèwòsàn First Cardiologist, tó wà nílùú Èkó, lẹ́yìn tó ní àrùn Kofi-19.

Ẹni àádọ́rin ọdún olóògbé Abíọ́lá Ajímọ̀bi ko tó tẹ́rí gbaṣọ.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED FOOL in Your ancestral Land.

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED Harlequin in Your ancestral Land.

The quote for today is a page from Toyin Falola’s book, ‘Yoruba Warlords of the 19th Century’. To a lot of Yoruba Muslims. Islam means servitude to Usman Dan Fodio’s estate at Sokoto. They indulge in the same idiocy that led to the fall of the great Hausa civilization. Many Yoruba Muslims from Oyo are a dangerously brainwashed set of people that would pose future danger for the preservation of Yorubaland like their ancestors who pledged allegiance to Ilorin and ...