Home / Art / Àṣà Oòduà / Ayeye Ojo Ibi Oba Lamidi
alafin oyo

Ayeye Ojo Ibi Oba Lamidi

Oba Alhamis Olayiwola Atanda Adeyemi, Alaafin ti ilu Oyo, pe eni odun metadinlogorin (77) lojo keedogun osu kewaa odun yii loke eepe.

Ayeye ojo ibi Oba Lamidi ni Omooba Akeem Adeyemi, eni to je okan lara awon omo ile gbimo asoju-sofin to wa l’Abuja se fun baba re lati fi dupe fun didasi ti Edua oke da baba re si.

Lara awon eto to waye ni ifilole gbongan nla kan nibi ti awon odo ilu naa yoo ti maa ko nipa imo ayarabiasa komputa.

Awon ori ade naa o gbeyin kaakiri ile Yooba, eleyii ti won dide lati bu ola oun iyi fun omo bibi inu Adeniran. Lara awon oba alade ti won ye Alaafin si ni Oba Osolo ti Isolo, Oba Kabiru Adelaja ati akegbe re lati ilu Eko, Oba Idowu Abiodun Oniru.

Ojo keedogun osu kewaa odun 1938 ni won bi Oba Lamidi. Ojo kejidinlogun osu kokanla odun 1970 lo gori ite baba re leni odun mejilalogbon (32).

Oba Lamidi Olayiwola to je okan lara awon oba alagbara ju lo ni ile Yoruba naa ni alaga igbimo lobaloba ipinle Oyo.

Olarewaju Adepoju, okan lara awon akewi ile Yoruba, se apejuwe Oba Lamidi lodun 1980, ni akoko odun kewaa oba Lamidi lori ite, gege bi Oosa yato si igbakeji Oosa ti awon eniyan n pe e.

About admin

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED FOOL in Your ancestral Land.

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED Harlequin in Your ancestral Land.

The quote for today is a page from Toyin Falola’s book, ‘Yoruba Warlords of the 19th Century’. To a lot of Yoruba Muslims. Islam means servitude to Usman Dan Fodio’s estate at Sokoto. They indulge in the same idiocy that led to the fall of the great Hausa civilization. Many Yoruba Muslims from Oyo are a dangerously brainwashed set of people that would pose future danger for the preservation of Yorubaland like their ancestors who pledged allegiance to Ilorin and ...