Home / Art / Àṣà Oòduà / Ẹ kéde iye ọlọ́pàá tó gba rìbá, kí ẹ tó má a yin ra a yín… Aráàlú sọ fún iléeṣẹ́ ọlọ́pàá

Ẹ kéde iye ọlọ́pàá tó gba rìbá, kí ẹ tó má a yin ra a yín… Aráàlú sọ fún iléeṣẹ́ ọlọ́pàá

Ẹ kéde iye ọlọ́pàá tó gba rìbá, kí ẹ tó má a yin ra a yín… Aráàlú sọ fún iléeṣẹ́ ọlọ́pàá

Èsì àwọn ọmọ Nàìjíríà tó tẹ̀lé bí iléèṣẹ́ ọlọ́pàá ṣe yin ara rẹ̀
Lórí káàdì tí wọ́n fi síta lójú òpó ayélujára Twitter wọn, iléeṣẹ́ ọlọ́pàá sọ pé káàdì náà jẹ́ àfihàn àkójọpọ̀ àwọn àṣeyọrí wọn láàrin ọjọ́ kẹrìndínlógún, oṣù Kínní, ọdún 2019 sí ọjọ́ kẹrìndínlógún, oṣù Kínní, ọdún 2020.

Wọ́n tọ́ka sí àwọn ‘ẹ̀ka’ bí àwọn afurasí, ọmọ ẹlẹ́gbẹ́ òkuǹkùn, tí ọwọ́ tẹ̀, tó fi mọ́ iye ọkọ̀ tí wọ́n jígbé, ṣùgbọ́n tí ọlọ́pàá gbà padà, àwọn afurasí ajínigbé àti adigunjalè, tó fi mọ́ iye nǹkan ìjà olóró tí wọ́n rí gbà.

Ṣùgbọ́n ṣá, bí àwọn ọmọ Nàìjíríà kan ṣe ń gbóríyìn fún àwọn ọlọ́pàá ni àwọn kan ń sọ pé àwọn ọmọ Nàìjíríà ló yẹ kó fi irú káàdì ìgbéléwọ̀n náà síta, kìí ṣe iléeṣẹ́ ọlọ́pàá.

Bákan náà ni àwọn kan tún ń sọ, paàpá lábẹ́ Ìkéde iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ọ̀hún pé, ó yẹ kí wọ́n ó kọ iye àṣìta ìbọn ọlọ́pàá tó pa aráàlú, rìbá gbígbà, iye àwọn ọ̀dọ́ tí ọlọ́pàá fìyà jẹ lọ́nà àìtọ́, àti àwọn ẹ̀sùn mìíràn tí aráàlú fi ń kàn àwọn ọlọ́pàá sí orí káàdì náà.

Yàtọ̀ sí èyí, àwọn kan sọ pé ó yẹ kí wọ́n kọ iye afurasí tí ọ̀rọ̀ wọn wà nílé ẹjọ́, àti àwọn tó ti gba ìdájọ́ s’órí káàdì ìgbéléwọ̀n náà.

Àwọn kan tilẹ̀ sọ pé kò dára bí wọ́n ṣe gbé káàdì ìgbéléwọ̀n náà, tó ṣàfíhàn ọjọ́ kẹrìndínlógún oṣù Kínní, ọdún 2019 sí ọjọ́ kẹrìndínlógún oṣù Kínní, ọdún 2020, jáde ní ọjọ́ kẹsàn án, oṣù Kínní, 2020.

Títí di àkókò yìí, iléeṣẹ́ ọlọ́pàá kò tíì f’èsì sí ìkankan.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED FOOL in Your ancestral Land.

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED Harlequin in Your ancestral Land.

The quote for today is a page from Toyin Falola’s book, ‘Yoruba Warlords of the 19th Century’. To a lot of Yoruba Muslims. Islam means servitude to Usman Dan Fodio’s estate at Sokoto. They indulge in the same idiocy that led to the fall of the great Hausa civilization. Many Yoruba Muslims from Oyo are a dangerously brainwashed set of people that would pose future danger for the preservation of Yorubaland like their ancestors who pledged allegiance to Ilorin and ...