Home / Art / Àṣà Oòduà / Awọn Olùgbé Ìpínlè Èkó Pè Fún Ìpàdé, Bí Ìjọba Ìpínlẹ̀ ÈKó Ṣe Sí Atẹ Ètò Tuntun Tí Wọn Lè Gbà Sọrọ
ipinle eko

Awọn Olùgbé Ìpínlè Èkó Pè Fún Ìpàdé, Bí Ìjọba Ìpínlẹ̀ ÈKó Ṣe Sí Atẹ Ètò Tuntun Tí Wọn Lè Gbà Sọrọ

Àwọn Olùgbé Ìpínlè Èkó pè fún Apero, bí Ìjọba Ìpínlẹ̀ Èkó ṣe ṣètò àwọn Nọmba ẹrọ ibanisọrọ mẹta t’awọn aráàlú lè pe sí tí wọn yóò tún bá àwọn oṣiṣẹ Ọba sọrọ.
Àwọn Nọmba ẹrọ ibanisọrọ métèèta jẹ tí Ilé -Ise tó n mojuto Òrò awọn Ọdọ àti Ìdàgbàsókè àwọn ohun igbafe, awọn Nọ́mbà náà ni (+2347077178295), Ilé -Ise Ìròyìn àti Ọgbọn Atinuda ní,(+2348119655788) Nọ́mbà ẹrọ ibanisọrọ Ofiisi tó n mojuto Òrò ètò Òsèlú, Ẹka Isofin àti Ọrọ awọn aráàlú ni (+2348025224347).

Laarin wákàtí Merinlelogun tí wọn sí àwọn Nọmba ìpè ẹrọ ibanisọrọ náà, o le ní igba àwọn aráàlú tí wọn ti pe s’awọn ilé-iṣẹ́ métèèta náà. Awọn èèyàn tí pe ni wọn sọrọ nípa àlàáfíà tí o j’ọba lásìkò ifehonu hàn tí o wáyé láì pé, N’ipinle Yìí, wá rọ, Gómìnà Babajide Sanwó-Olu pé kí wọ́n jẹ k’awọn ètò tí wọn n ṣe tunbo máa tẹsiwaju, l’ojuna àti dín ìnira t’awọn aráàlú n kojú kù.

Ohun tí o l’eke nínú nnkan tí wọn fẹ ní ìdápadà ọjà Àìkú tí wọn n ṣe, ìyẹn “Ounjẹ Èkó” tí wọn n ṣe káàkiri Ìpínlè yìí; iko Meedogbon nínú ida ogorun tí wọn yọ kúrò nínú owó ọkọ si wà sibẹ àti ètò ìlera ọfẹ kò gbẹyin.

Ọkan lára àwọn Olùgbé Ìpínlè yìí ra owó ebe sí, Gómìnà Babajide Sanwó-Olu pé kí wọ́n dá adinku owó ọkọ BRT padà. Irinajo láti agbègbè Ipaja nínú ọkọ BRT tí wọn dinku láti Ẹgbẹrin Náírà, ìyẹn ₦800, di Ẹgbẹta Náírà, ìyẹn ₦600, tún tí padà sí Ẹgbẹrin Náírà bayii, inú wa yóò dun bí Gómìnà bá lè pàṣẹ f’awon alakoso ọkọ BRT kí wọ́n dín owó náà kù padà. Èyí yóò jẹ k’owo ọkọ r’oju.

Akékòó kan láti Ilé Ẹkọ Gíga Fasiti Ìpínlè Èkìtì, Ayomide Olarinmoye, bèrè nípa owó T’ijoba Àpapọ fẹ fún àwọn akékòó.
Nkechi Ajubike sọrọ nípa ebi tó n b’awọn aráàlú finra, wá mú amoran wà nípa àwọn ohun tí wọn lè ṣe f’odindi oṣù mẹ́fà tí yóò dín ìnira ètò ọrọ Ajé t’awọn aráàlú n kojú kù.

Ewe, Komisona Ìròyìn àti Ọgbọn Atinuda, Ògbéni Gbenga Omotoso sọ pé, bo ṣe ye kí o rí nìyẹn. Ìpínlè Èkó Nìyí. A o fayegba Àpérò bóri Rogbodiyan, l’eyii tí kìí ṣe ònà wa.
Komisona náà tẹnumọ pé, ìṣàkóso Ìjọba Gómìnà Sanwó-Olu yóò tunbo máa gbé agbára wọ̀ awọn odo at’awọn akékòó nípa ṣíṣe ìdánilékòó fún wọn, yóò tún pèsè àwọn ohun èlò iṣẹ f’awon tí wọn bá fẹ s’owo.

“Ètò biba awọn ọdọ sọrọ yóò di àlàfo tí o wà láàárín àwọn ọdọ àti awọn tó n ṣàkóso Ìjọba” Ògbéni Omotoso sọrọ yìí.

Agbega Ìpínlè Èkó Ajumọṣe Gbogbo wa ni

Ijoba Ìpínlè Èkó.

@jidesanwoolu
@drobafemihamzat
@gbenga_omo
@gboyegaakosile
@BSaluHundeyin
@Mr_JAGs

@Mo_ogunlende

LASG #AGreaterLagosRising

About ayangalu

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

minister

Nigerian foreign minister urges West to focus on its security issues

Earlier, the US and UK issued warnings about the risks of staying in Nigeria amid anti-government protests, urging their citizens to refrain from traveling to the country for the time being. 💬 “We have seen from events as they unfolded in the United Kingdom—we’re also seeing in the US, with the shooting of a presidential candidate—that risk or danger exists everywhere. It’s how you navigate it that is different,” Yusuf Tuggar told a Western media outlet. “We’re not saying that ...