Home / Art / Àṣà Oòduà / ERÍWO YÀ! ERÍWO YÀ!! ERÍWO YÀ!!!

ERÍWO YÀ! ERÍWO YÀ!! ERÍWO YÀ!!!

Gbogbo ẹ̀yin Babaláwo àti Oníṣẹ̀ṣe lápapọ̀; Ojú rẹ rèé o : Babaláwo Babájídé Ọ̀ṣúnníyì (Olúwo Jọ̀gbọ̀dọ́ Ọ̀rúnmìlà).

Ní òní yìí ni ìgbẹ́jọ́ ẹ̀sùn oyún síṣẹ́ fún ọ̀dọ́mọbìnrin tó ṣẹ̀ṣẹ̀ padà sí ìdí Ifá / Ìṣẹ̀ṣe (lẹ́yìn ikú Baba rẹ ní bí ọdún mélòó sẹ́yìn) ní èyí tó fẹ́ la ikú òjijì lọ láì ṣe ìtọ́jú rẹ̀ (ní èyí tó jẹ́ ìgbà kẹ̀jọ́ fún ọ̀dọ́mọbìnrin mẹ́jọ ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀) tí ẹgbẹ́ Society for the Ifá Practice in Nigeria (SIPIN) fi kan Babaláwo Babájídé Ọ̀ṣúnníyì alias Olúwo Jọ̀gbọ̀dọ́ Ọ̀rúnmìlà bẹ̀rẹ̀ nílé Awo ilẹ̀ Ìbàdàn, ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́.

Ṣùgbọ́n sí ìyàlẹ́nu gbogbo àwọn Olóyè Awo ilẹ̀ Ìbàdàn, Babaláwo Jídé Ọ̀ṣúnníyì kọ̀ jálẹ̀ láti jẹ́ ìpè Ọ̀ṣẹ́ Méjì ní Ìbàdàn, ó ní ọmọ Ọ̀yán ní ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun ni òun, àti pé òun kàn ń gbé; òun sì ń tún ṣe Awo ní ìlú Ìbàdàn lásán ní (bó tilẹ̀ jẹ́ pé ọmọ bíbí ìlú Ìbàdàn ní ìyá tó bíi).

Ilé Awo wá ń béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé ṣé ìdí nìyí tí ó fi fẹ́ ba Ilẹ̀ Ìbàdàn jẹ́ nìyẹn?

Ilé Awo Ilẹ̀ Ìbàdàn wá paá láṣẹ fún un àti fún àwọn ẹbí rẹ̀ láti wá jẹ́ ìpè Ọ̀ṣẹ́ Méjì tí ilẹ̀ Ìbàdàn ní ìtàdógún Awo tó ń bọ̀.

Adérèmí Ifáòleèpin Adérèmí
Founder and Chief Coordinating Officer
Society for the Ifá Practice in Nigeria (SIPIN).

About Awoyemi Bamimore

VI

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

Europe at the Point Between Glory and Decadence

A Legacy Shaped by War and Reinvention Europe today stands like an aging performer on a global stage it once commanded. Its architecture still stirs awe, its philosophy continues to shape international law, and its revolutions echo through the foundations of modern governance. Yet beneath the surface lies a continent in quiet decline. From the trenches of the Thirty Years’ War to the red carpets of the Congress of Vienna, from the carnage of Verdun to the cold arithmetic of ...