Home / Art / Àṣà Oòduà / Ìjàpá Tó Wà Ní Ààfin Ṣọ̀ún Ògbómọ̀ṣọ́ (Alàgbà) Ti Papòdà
ijapa

Ìjàpá Tó Wà Ní Ààfin Ṣọ̀ún Ògbómọ̀ṣọ́ (Alàgbà) Ti Papòdà

Ìṣe èèyàn ,ìṣe ẹranko, Ìjàpá tó wà ní ààfin Ṣọ̀ún Ògbómọ̀ṣọ́ Alàgbà ti papòdà lẹ́ni ojilelọọdunrun ọdún ó lé mẹrin lóke eèpẹ̀ .

Fẹ́mi Akínṣọlá

Toyin Ajamu, to jẹ akọwe agba ni Ààfin Kabiyesi Ṣọun ti ilẹ Ogbomọṣọ ti bùn ún akọ̀ròyìn gbọ́ pé ijapa naa ti apele rẹ n jẹ Alàgbà jade laye lẹyin aisan ranpẹ.
O ni nǹkan bi aago mọkanla abọ owurọ yìí ni ọlọjọ de ba a.
Ajamu ṣalaye pe, idi ti wọn fi n pe ijapa naa to sílẹ wọ ní Alàgbà jẹ nitori ọjọ ori i rẹ.
O tẹsiwaju pe erongba ilu Ogbomọṣọ ni lati gbe iyoku ara ijapa ọhun si gbagede, ti gbogbo eeyan yoo si le ma wo o nilẹ yi ati loke okun.
Ajamu ni ijapa naa ti gbe ni aafin Ṣọun fun ọpọlọpọ ọdun,
orukọ rẹ ni Alagba.O ni awọn òṣìṣẹ́ lati aafin Kabiyesi to n tọju oun nikan. Oṣiṣẹ meji tabi ju bẹẹ lọ lo n tọju u rẹ. Lati kekere ni àwọn kan ti n tọju rẹ ti wọn si dagba sẹ́nu ẹ.
Baba Kabiyesi oni to jẹ Jagunjagun lo pade rẹ leti igbo to si mu u bọ wale latoju ogun.


Gbogbo ounjẹ ti eniyan n jẹ loun naa n jẹ to fi mọ eso bii;Ibẹpẹ, Ọpẹ Oyinbo, ,Ọgẹdẹ. bakan naa, o n jẹ amala, irẹsi, dodo atẹwa ati bẹẹ bẹẹ lọ. Akọ̀ròyìn Owurọ rii gbọ pé ijapa naa ti inagijẹ rẹ n jẹ Alàgbà, ti di gbajúgbajà ,irawọ ọsan ti okiki i rẹ si tan tayọ ilu Ogbomọṣọ debii pé, wọn n wa sabẹwo si Alàgbà ,lati àwọn ilẹ okeere,nipa bẹẹ Alàgbà ti mú okiki ba ilu Ogbomọṣọ .

http://iroyinowuro.com.ng/

About ayangalu

VI

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

Omisore

Àwàdà kẹrí-Kẹrì ni àwọn kọmití tó ní mi ò lè díje du ipò gómìnà APC ni 2026 n ṣe – Omisore

Yínká Àlàbí Awọn kọmiti to n ṣe àyẹ̀wò awọn oludije du ipo gomina labẹ ẹgbẹ́ oselu APC ti ja igbakeji gomina tẹlẹ ni ipinle Osun, Alagba Iyiola Omisore ati awọn mẹfa miiran.Wọn ni iwe wọn ko pe lati dije du ipo gomina ipinlẹ naa. Awọn mẹfẹẹfa to ku naa ni – Babatunde Oralusi, Oyedotun Babayemi, Dr. Akin Ogunbiyi, Benedict Alabi, Adegoke Rasheed Okiki, ati Senator Babajide Omoworare.Iyiola Omisore ni awada Kẹri-Kẹri ni awọn kọmiti naa n se nitori ti wọn ...