Home / Art / Àṣà Oòduà / ORÍLÈ ÈDÈ MI
Nigeria Flag

ORÍLÈ ÈDÈ MI

ORÍLÈ ÈDÈ MI

Nàìjíríà ìlú mi pàtàkì
Ìlú t’ókún fún ogbón
Pèlú òpòlopò àwon òjògbón
Ilé ogbón
Tí a ti n hun àgbòn ìwà ìbàjé
S’ogúndogójì di ààyò àwon òdó
Òsèlú di ohun wón k’èyìn sí
Egbé òsèlú di ìkan kò gbé’kan
“Birds of a feather”
Bí àwon olóyìnbó se máa n so
Iró n pa’ró fún iró
Ìtànje lásán làsàn
Ní àti ojó tí a ti gba òmìnira
Omi ìnira ni àwon olórí wa n fún wa mu
Màá se eléyìí
Màá se tòún
Sí bè…
Ìsé òun òsì
Kò tán ní àwùjo wa
Kílódé, kí ló se wá
PDP se ìjoba ó ya mó won lówó
APC ò sun wòn
Tani yóò gbà wá ní owó àwon jegúdú jerá wònyí
Tí wón n pe ra won ní olórí wa
Àkókò náà tó wàyìí
Ó tó géé oní bàtá kan kìí dá Orin
Èyin òdó, àsìkò náà ti tó
Láti GBA ìjoba
Ní owó àwon alágbára a tó kú má kùú a mònà òrun má lo
2019! E jé kí á dìbò fún
Òdó langba kí ìtèsíwájú leè
Dé bá gbogbo wa.

About Awoyemi Bamimore

VI

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

Omisore

Àwàdà kẹrí-Kẹrì ni àwọn kọmití tó ní mi ò lè díje du ipò gómìnà APC ni 2026 n ṣe – Omisore

Yínká Àlàbí Awọn kọmiti to n ṣe àyẹ̀wò awọn oludije du ipo gomina labẹ ẹgbẹ́ oselu APC ti ja igbakeji gomina tẹlẹ ni ipinle Osun, Alagba Iyiola Omisore ati awọn mẹfa miiran.Wọn ni iwe wọn ko pe lati dije du ipo gomina ipinlẹ naa. Awọn mẹfẹẹfa to ku naa ni – Babatunde Oralusi, Oyedotun Babayemi, Dr. Akin Ogunbiyi, Benedict Alabi, Adegoke Rasheed Okiki, ati Senator Babajide Omoworare.Iyiola Omisore ni awada Kẹri-Kẹri ni awọn kọmiti naa n se nitori ti wọn ...