Home / Art / Àṣà Oòduà / Àwọn Fíìmù Òde Òní Ń Kọ́mọ Lólè Àti Ọ̀pọ̀ Ìwà Burúkú – Iyabo Ogunsola
Àwọn Fíìmù Òde Òní Ń Kọ́mọ Lólè Àti Ọ̀pọ̀ Ìwà Burúkú – Iyabo Ogunsola

Àwọn Fíìmù Òde Òní Ń Kọ́mọ Lólè Àti Ọ̀pọ̀ Ìwà Burúkú – Iyabo Ogunsola

Àwọn fíìmù òde òní ń kọ́mọ lólè àti ọ̀pọ̀ ìwà burúkú

Fẹ́mi Akínṣọlá
Ṣé àwọn àgbà bọ̀ wọ́n ní ẹgbẹ́ burúkú ba ìwà rere jẹ́.

Ajíyìnrere Felicia Iyabode Ogunsola tí gbogbo èèyàn mọ̀ sí Efúnsetán Aníwúrà, Ìyálọ́de ìlú Ìbàdàn nínú eré, ti kìlọ̀ fáwọn òṣèré tíátà láti dẹ́kun àṣà ṣíṣíra sílẹ̀ nínú fíímù.

Efúnsetán ní àṣà burúkú gbáà ni.
Ó ṣàlàyé pé kìí ṣe ohun tó dára kí àṣírí ọyàn máa hàn síta,iṣẹ́ Èṣù ni.

Ó fikún ọ̀rọ̀ rẹ̀ pé kò sí ohun tó jọ bẹ́ẹ̀ rárá nígbà tí òun fi ń ṣeré lábẹ́ ògbóǹtarìgì òṣèré, olóògbé Iṣhola Ogunsola tí ọ̀pọ̀ mọ̀ sí Isho Pepper.

Iyabode Ogunsola ní àṣà àìbìkítà, àti àìlójútì gbá à ni.
Ó ní àṣà àwọn òyìnbó ni àwọn òṣèré òde òní ti gbé wọ eré tíátà Yorùbá.

Àgbà òṣèré náà ní àṣà kí á máa yìnbọn pò pò pò nínú fíímù ló kọ́ àwọn ọmọ lólè láyé òde òní, dípò kí àwọn ọmọdé máa rí ẹ̀kọ́ kọ́ níbẹ̀.

Ó rọ ọ̀pọ̀ òṣèré tí wọn kò tíì lọ kẹ́kọ́ọ̀ eré tíátà ṣíṣe níbì kankan pé kí wọ́n yára tètè lọ se bẹ́ẹ̀ nítorí kò sí òṣèré kan tí kò kẹ́kọ́ọ̀ lábẹ́ ẹnìkan nígbà tàwọn náà.

About ayangalu

VI

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

Omisore

Àwàdà kẹrí-Kẹrì ni àwọn kọmití tó ní mi ò lè díje du ipò gómìnà APC ni 2026 n ṣe – Omisore

Yínká Àlàbí Awọn kọmiti to n ṣe àyẹ̀wò awọn oludije du ipo gomina labẹ ẹgbẹ́ oselu APC ti ja igbakeji gomina tẹlẹ ni ipinle Osun, Alagba Iyiola Omisore ati awọn mẹfa miiran.Wọn ni iwe wọn ko pe lati dije du ipo gomina ipinlẹ naa. Awọn mẹfẹẹfa to ku naa ni – Babatunde Oralusi, Oyedotun Babayemi, Dr. Akin Ogunbiyi, Benedict Alabi, Adegoke Rasheed Okiki, ati Senator Babajide Omoworare.Iyiola Omisore ni awada Kẹri-Kẹri ni awọn kọmiti naa n se nitori ti wọn ...