Home / Art / Àṣà Oòduà / Ìjọba Àpapọ̀ Kò Gbẹ́sẹ̀lẹ̀ Lé Owó Tó Tọ́ Sáwọn Ìjọba Ìbílẹ̀ L‘ọyọ
Governor Seyi Makinde

Ìjọba Àpapọ̀ Kò Gbẹ́sẹ̀lẹ̀ Lé Owó Tó Tọ́ Sáwọn Ìjọba Ìbílẹ̀ L‘ọyọ

Ìjọba àpapọ̀ kò gbẹ́sẹ̀lẹ̀ lé owó tó tọ́ sáwọn ìjọba ìbílẹ̀ l‘Ọyọ

Fẹ́mi Akínṣọlá

Lórí ọ̀rọ̀ kan tó gbà gboro kan pé àgbẹjọrò àgbà orilẹ̀-èdè Naijiria, Abubakar Malami ti pàṣẹ fún gómìnà ìpínlẹ̀ Oyo láti gba àwọn alága káńṣù ti wọ́n yọ nípò pada, Ìjọba Ọyọ ti fèsì lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà.

Nígbà tó ń sẹ̀rí ọ̀rọ̀ náà, Akọ̀wé ìkéde ìjọba ìpińlẹ̀ Oyo, Ọgbẹ́ni Taiwo Adisa ní, ìrọ tó jìnà sí òtítọ ni nítori pé òun kò tí ì rí lẹ́ta kankan tó jọ bẹ́ẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Malami.
Ó fí kún un pé kò sí ìgbà kankan tí Malami jáde láti sọ pé òun kọ lẹ́tà ránṣẹ́ si ìpínlẹ̀ Oyo, pẹ̀lú àfikún pé, ó se pàtàki ki àwọn akọ̀ròyìn máa ṣe ìwádìí wọ́n dáradára, ki wọ́n tó máa tan ìròyìn tí kò fi ìdí múlẹ̀ káàkiri.

Lórí àhesọ ọ̀rọ̀ kan tó sọ pé, ìjọba ìpinlẹ̀ Oyo kò rí owó gbà láti ọ̀dọ̀ ìjọba àpapọ̀ fún àwọn ìjọba ìbilẹ̀, nítori pé àwọn Alága fìdíẹ ni wọ́n fi sí ìjọba Káńsù Adisa ní òfo ọjọ́ kejì ọjà ni ọ̀rọ̀ ọ̀hún.

” Ẹni tí wọ́n bá nà ló yẹ kí ara máa ta, tí ìjọba ìpínlẹ̀ Ọyọ kò bá rí owó gbà, ẹnu ìjọba ìpínlẹ̀ ni ẹ ó ti gbọ́ kìí ṣe ẹnu àwọn ìròyìn ẹlẹ́jẹ̀. Nítorí náà, òfúùtù fẹ́ẹ̀tẹ̀ ni Ìròyìn tó ní àwọn Ìjọba ìbílẹ̀ ní Ọyọ kò rí owó tó tọ́ sí wọn gbà láti ọ̀dọ̀ Ìjọba àpapọ̀.”

About ayangalu

VI

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

amoke

Itan Omooba Amoke

Omooba obinrin kan gbe ni ilu alayo, orewa pupo ju oruko re si nje Amoke ni ile Yoruba atijo. Orewa pupo debi pe gbogbo okunrin ilualayo niwon ko enu ife si, koda awon okunrin ilu agbegbe won gan o gbeyin. Amoke n ma bu gbogbo awon okunrin ti oba soro ife leti re koda atun pariwo lewon lori. Oro yin kan Oba ilu ti oje baba re lomi nu. Loru ojo kan, Oba ji Amoke sile o de ba so ...