Ẹ̀bùn Edùmarè ni ọmọ
Ẹ̀rí ìfẹ́ rẹ̀ sí wa ni wọ́n
Èdùmàrè à ń bẹ̀ ọ́
Bá wa wo àwọn èwe yè
Fi wọ́n fún àwọn tí ń wojú rẹ fún ẹ̀bùn wọn
Má ṣe jẹ́ kí wọ́n kú mọ́ àwọn òbí wọn lọ́wọ́
Èyí a wí yìí, kárọ̀ rọ̀ mọ́ ọn.
@AlamojaYoruba
Tírélà jábọ́ láti orí afárá l’Eko, rún Korope méji pa Fẹ́mi Akínṣọlá Aago mẹ́sàn-án òwúrọ̀ ló ń lọ lu lọjọ Àbámẹ́ta, ọjọ́ kẹrìndínlọ́gbọ̀n, oṣù Kerin 2025, tírélà kan fi jábọ́ láti orí afárá Pen Cinema, Agege, l’Ekoo, tó sì run ọkọ̀ Kórópe méjì tó jábọ́ lé lórí pa. Ajọ Lagos State Traffic Management Authority (LASTMA), to n ri si igbokegbodo ọkọ l’Ekoo, fidi iṣẹlẹ yii mulẹ. Atẹjade kan ti Adari iṣẹlẹ bi eyi ati ilaniloye ni LASTMA, Adebayo Taofiq, fi ...