Home / Art / Àṣà Oòduà / Ìjàpá Tó Wà Ní Ààfin Ṣọ̀ún Ògbómọ̀ṣọ́ (Alàgbà) Ti Papòdà
ijapa

Ìjàpá Tó Wà Ní Ààfin Ṣọ̀ún Ògbómọ̀ṣọ́ (Alàgbà) Ti Papòdà

Ìṣe èèyàn ,ìṣe ẹranko, Ìjàpá tó wà ní ààfin Ṣọ̀ún Ògbómọ̀ṣọ́ Alàgbà ti papòdà lẹ́ni ojilelọọdunrun ọdún ó lé mẹrin lóke eèpẹ̀ .

Fẹ́mi Akínṣọlá

Toyin Ajamu, to jẹ akọwe agba ni Ààfin Kabiyesi Ṣọun ti ilẹ Ogbomọṣọ ti bùn ún akọ̀ròyìn gbọ́ pé ijapa naa ti apele rẹ n jẹ Alàgbà jade laye lẹyin aisan ranpẹ.
O ni nǹkan bi aago mọkanla abọ owurọ yìí ni ọlọjọ de ba a.
Ajamu ṣalaye pe, idi ti wọn fi n pe ijapa naa to sílẹ wọ ní Alàgbà jẹ nitori ọjọ ori i rẹ.
O tẹsiwaju pe erongba ilu Ogbomọṣọ ni lati gbe iyoku ara ijapa ọhun si gbagede, ti gbogbo eeyan yoo si le ma wo o nilẹ yi ati loke okun.
Ajamu ni ijapa naa ti gbe ni aafin Ṣọun fun ọpọlọpọ ọdun,
orukọ rẹ ni Alagba.O ni awọn òṣìṣẹ́ lati aafin Kabiyesi to n tọju oun nikan. Oṣiṣẹ meji tabi ju bẹẹ lọ lo n tọju u rẹ. Lati kekere ni àwọn kan ti n tọju rẹ ti wọn si dagba sẹ́nu ẹ.
Baba Kabiyesi oni to jẹ Jagunjagun lo pade rẹ leti igbo to si mu u bọ wale latoju ogun.


Gbogbo ounjẹ ti eniyan n jẹ loun naa n jẹ to fi mọ eso bii;Ibẹpẹ, Ọpẹ Oyinbo, ,Ọgẹdẹ. bakan naa, o n jẹ amala, irẹsi, dodo atẹwa ati bẹẹ bẹẹ lọ. Akọ̀ròyìn Owurọ rii gbọ pé ijapa naa ti inagijẹ rẹ n jẹ Alàgbà, ti di gbajúgbajà ,irawọ ọsan ti okiki i rẹ si tan tayọ ilu Ogbomọṣọ debii pé, wọn n wa sabẹwo si Alàgbà ,lati àwọn ilẹ okeere,nipa bẹẹ Alàgbà ti mú okiki ba ilu Ogbomọṣọ .

About ayangalu

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED FOOL in Your ancestral Land.

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED Harlequin in Your ancestral Land.

The quote for today is a page from Toyin Falola’s book, ‘Yoruba Warlords of the 19th Century’. To a lot of Yoruba Muslims. Islam means servitude to Usman Dan Fodio’s estate at Sokoto. They indulge in the same idiocy that led to the fall of the great Hausa civilization. Many Yoruba Muslims from Oyo are a dangerously brainwashed set of people that would pose future danger for the preservation of Yorubaland like their ancestors who pledged allegiance to Ilorin and ...