Home / Art / Àṣà Oòduà / llé iṣẹ́ ọ̀lọ́pàá ,ẹ dá ìgbaniwọlé tí ẹ gùnlé dúró… Àṣẹ ilé ẹjọ́
policeman

llé iṣẹ́ ọ̀lọ́pàá ,ẹ dá ìgbaniwọlé tí ẹ gùnlé dúró… Àṣẹ ilé ẹjọ́

llé iṣẹ́ ọ̀lọ́pàá ,ẹ dá ìgbaniwọlé tí ẹ gùnlé dúró… Àṣẹ ilé ẹjọ́

Fẹ́mi Akínṣọlá

Ṣé àwọn àgbà ní ilé tí a fi itọ́ mọ, ìrì ni yóò wo. Ọbẹ̀ tí a fi èké pilẹ̀ ẹ rẹ̀, í í ru paná ni bẹ́ẹ̀ gẹ́lẹ́ ni ọ̀rọ̀ rí, nígbà tílé ẹjọ́ gígá nílùú Abuja pàsẹ pé kí àjọ ọlọpàá dá ètò ìgbànisísẹ́ ẹgbẹ̀run mẹ́wàá tí wọ́n ń ṣe lọ́wọ́ dúró.
Adajọ Inyang Ekwo ló fi idájọ náà janlẹ̀ pé kí wọ́n dáa dúró títí tí igbẹ́jọ́ tí àjọ ọlọpàá pe.
Èyí wáye lẹ́yin tí wọ́n so igbẹ́jó náà rọ̀. Adájọ́ àgbà Abubakar Malami wà nínú ejọ náà.
Àwọn míràn nínú ìgbẹ́jọ́ náà ni , Ọ̀gá àgbà ọlọpàá àti mínísita fún ọ̀rọ ọlọpàá.
Adájọ́ Ekwo ní gbogbo àwọn ti ọ̀rọ̀ náà kàn ní wọn gbọdọ̀ tẹ̀lé ìdájọ náà títí yóò fi pari ọ̀rọ̀ naa.

Wàhálà ejọ́ yìí bẹ̀rẹ̀ lásìkò tí àjọ ọlọpàá fẹ̀sùn kan ilé iṣẹ́ ọlọpàá pé wọ́n já ètò igbànisísẹ́ náà gbà mọ àwọn lọ́wọ́.
Àjọ ọlọ́pàá fẹ̀sùn kan ilé iṣẹ́ ọlọpàá pé wọ́n ti tọwọ́bọ ètò ìgbàniwọle náà nípa àyípada àwọn orúkọ nínú iwé orúkọ.
Tí ẹ ò bá gbàgbé ètò ìgbaniwọlé ọlọ́pàá náà bẹ̀rẹ̀ ní òpin ọdún tó kọjá.

http://iroyinowuro.com.ng/2019/10/26/lle-i%e1%b9%a3e-olopaa-e-da-igbaniwole-ti-e-gunle-duro-a%e1%b9%a3e-ile-ejo/

About ayangalu

VI

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

Omisore

Àwàdà kẹrí-Kẹrì ni àwọn kọmití tó ní mi ò lè díje du ipò gómìnà APC ni 2026 n ṣe – Omisore

Yínká Àlàbí Awọn kọmiti to n ṣe àyẹ̀wò awọn oludije du ipo gomina labẹ ẹgbẹ́ oselu APC ti ja igbakeji gomina tẹlẹ ni ipinle Osun, Alagba Iyiola Omisore ati awọn mẹfa miiran.Wọn ni iwe wọn ko pe lati dije du ipo gomina ipinlẹ naa. Awọn mẹfẹẹfa to ku naa ni – Babatunde Oralusi, Oyedotun Babayemi, Dr. Akin Ogunbiyi, Benedict Alabi, Adegoke Rasheed Okiki, ati Senator Babajide Omoworare.Iyiola Omisore ni awada Kẹri-Kẹri ni awọn kọmiti naa n se nitori ti wọn ...