Home / Art / Àṣà Oòduà / Mo Ti Fi Ẹjọ́ Abani Lórúkọjẹ́ Tó Fẹ́ Fi Àwòrán Ìhòòhò Mi S’órí Ìtàkùn Àgbáyé Sun Ìjọba – Waka Queen
Waka Queen

Mo Ti Fi Ẹjọ́ Abani Lórúkọjẹ́ Tó Fẹ́ Fi Àwòrán Ìhòòhò Mi S’órí Ìtàkùn Àgbáyé Sun Ìjọba – Waka Queen

À fi kí Ọlọ́run gbani lọ́wọ́ ẹni tó ń ṣọ́ni tá ò ṣọ́ o, ló dífá fún kójú má ríbi,gbogbo ara lòògùn rẹ̀, bí gbajúgbajà olórin wákà, Salawa Abẹni ti sọ pé, òun ti fi ẹjọ́ abani lórúkọ je tó fẹ́ fi àwòrán ìhòòhò òun léde lórí itàkùn àgbáyé sun Ìjọba.

Salawa ló sọ ọ̀rọ̀ yìí nínú ìfọ̀rọ̀wérọ̀ pẹ̀lú akọ̀ròyìn.

Ó ní òun kò mọ ẹni tó ṣe iṣẹ́ ibi ọ̀hún, ṣùgbọ́n bí ikú ilé ò pani, tòde kò lè pani.

Salawa sọ pé ọkùnrin náà bá òun ṣọ̀rọ̀ lórí ìkànnì WhatsApp, tó sì sọ pé kí òun fún un lówó, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, òun yóó fi àwòrán ìhòòhò rẹ̀ léde fún gbogbo ayé láti rí.

Gbajúgbajà olórin wákà náà ṣàlàyé pé ìṣẹ̀lẹ̀ náà kò tu irun kankan lara oun.

Lẹ́yìn náà ló sọ pé òun kò leè gbà kí ẹnikẹ́ni ba orúkọ òun jẹ́ lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún tó ti ń to orúkọ ọ̀hún jọ, ìdí rè é tí òun ṣe fi ọ̀rọ̀ náà tó àwọn agbófinró létí.

Ṣaájú ni Salawa ti fi ọ̀rọ̀ kan léde lójú òpó Instagram rẹ̀, níbi tó ti ṣàfihàn àtẹ̀ránṣẹ́ ti ọkùnrin náà, tó pe orúkọ ara rẹ̀ ní Jason tẹ̀ ẹ́ sí.

Ọkùnrin ọ̀hún ṣọ pé kí Salawa fún òun lówó, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, òun yóó fi àwòrán ìhòòhò Salawa léde fún gbogbo àgbáyé láti rí.

Lẹ́yìn èyí ni Salawa fún ra rẹ̀ wá fi àwòrán ọ̀hún léde.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

One comment

  1. oladipupo olaide .J.

    @fowosereomoba .Follow me and get followed back immediately

VI

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

Omisore

Àwàdà kẹrí-Kẹrì ni àwọn kọmití tó ní mi ò lè díje du ipò gómìnà APC ni 2026 n ṣe – Omisore

Yínká Àlàbí Awọn kọmiti to n ṣe àyẹ̀wò awọn oludije du ipo gomina labẹ ẹgbẹ́ oselu APC ti ja igbakeji gomina tẹlẹ ni ipinle Osun, Alagba Iyiola Omisore ati awọn mẹfa miiran.Wọn ni iwe wọn ko pe lati dije du ipo gomina ipinlẹ naa. Awọn mẹfẹẹfa to ku naa ni – Babatunde Oralusi, Oyedotun Babayemi, Dr. Akin Ogunbiyi, Benedict Alabi, Adegoke Rasheed Okiki, ati Senator Babajide Omoworare.Iyiola Omisore ni awada Kẹri-Kẹri ni awọn kọmiti naa n se nitori ti wọn ...