Home / Art / Àṣà Oòduà / Mo Ti Fi Ẹjọ́ Abani Lórúkọjẹ́ Tó Fẹ́ Fi Àwòrán Ìhòòhò Mi S’órí Ìtàkùn Àgbáyé Sun Ìjọba – Waka Queen
Waka Queen

Mo Ti Fi Ẹjọ́ Abani Lórúkọjẹ́ Tó Fẹ́ Fi Àwòrán Ìhòòhò Mi S’órí Ìtàkùn Àgbáyé Sun Ìjọba – Waka Queen

À fi kí Ọlọ́run gbani lọ́wọ́ ẹni tó ń ṣọ́ni tá ò ṣọ́ o, ló dífá fún kójú má ríbi,gbogbo ara lòògùn rẹ̀, bí gbajúgbajà olórin wákà, Salawa Abẹni ti sọ pé, òun ti fi ẹjọ́ abani lórúkọ je tó fẹ́ fi àwòrán ìhòòhò òun léde lórí itàkùn àgbáyé sun Ìjọba.

Salawa ló sọ ọ̀rọ̀ yìí nínú ìfọ̀rọ̀wérọ̀ pẹ̀lú akọ̀ròyìn.

Ó ní òun kò mọ ẹni tó ṣe iṣẹ́ ibi ọ̀hún, ṣùgbọ́n bí ikú ilé ò pani, tòde kò lè pani.

Salawa sọ pé ọkùnrin náà bá òun ṣọ̀rọ̀ lórí ìkànnì WhatsApp, tó sì sọ pé kí òun fún un lówó, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, òun yóó fi àwòrán ìhòòhò rẹ̀ léde fún gbogbo ayé láti rí.

Gbajúgbajà olórin wákà náà ṣàlàyé pé ìṣẹ̀lẹ̀ náà kò tu irun kankan lara oun.

Lẹ́yìn náà ló sọ pé òun kò leè gbà kí ẹnikẹ́ni ba orúkọ òun jẹ́ lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún tó ti ń to orúkọ ọ̀hún jọ, ìdí rè é tí òun ṣe fi ọ̀rọ̀ náà tó àwọn agbófinró létí.

Ṣaájú ni Salawa ti fi ọ̀rọ̀ kan léde lójú òpó Instagram rẹ̀, níbi tó ti ṣàfihàn àtẹ̀ránṣẹ́ ti ọkùnrin náà, tó pe orúkọ ara rẹ̀ ní Jason tẹ̀ ẹ́ sí.

Ọkùnrin ọ̀hún ṣọ pé kí Salawa fún òun lówó, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, òun yóó fi àwòrán ìhòòhò Salawa léde fún gbogbo àgbáyé láti rí.

Lẹ́yìn èyí ni Salawa fún ra rẹ̀ wá fi àwòrán ọ̀hún léde.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

One comment

  1. oladipupo olaide .J.

    @fowosereomoba .Follow me and get followed back immediately

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED FOOL in Your ancestral Land.

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED Harlequin in Your ancestral Land.

The quote for today is a page from Toyin Falola’s book, ‘Yoruba Warlords of the 19th Century’. To a lot of Yoruba Muslims. Islam means servitude to Usman Dan Fodio’s estate at Sokoto. They indulge in the same idiocy that led to the fall of the great Hausa civilization. Many Yoruba Muslims from Oyo are a dangerously brainwashed set of people that would pose future danger for the preservation of Yorubaland like their ancestors who pledged allegiance to Ilorin and ...