Home / Art / Àṣà Oòduà / Odun odun kan ko dun dun

Odun odun kan ko dun dun

Ko dun bi odun yi ri
Odun ti o dun ni odun ominira1960
Odun n dun ni dundun n dun
Orile-ede ti n San fun wara ati oyin
Orile-ede abinibi Nigeria
Adugbo ti n toro
omo ale ni ke ti i dagba
Ki lode ti iku wa di ponkan to o ro
Ti ibon n ro gbamugbamu
Losan-an gangan
Aaro kutukutu kuku ni isele
N la ti n se ti gongo ti n so
Titi di ojoale kerere
Bo ba doganjo
ibon o kan maa yoofin lenu ni
Alarinfesesi yoo si ti fi nnkan gbara
Ohun gbogbo a wa pa kese
Awon alakori bokoharam, Fulani….
Nibi ti iku ti gbe n pe iku ran nise
Loju alusi iji ti n gbe ketepe ogi
Iru itu wo lelekuku elubo le pa
olomokuuya, iku dohun amusere
Ere buruku, eree gele
Ibon wa se pe pe pe
Lara omo eniyan
E e si maa wo tikunle abiamo !
Nigeria nibo la n lo?

About Awoyemi Bamimore

VI

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

Omisore

Àwàdà kẹrí-Kẹrì ni àwọn kọmití tó ní mi ò lè díje du ipò gómìnà APC ni 2026 n ṣe – Omisore

Yínká Àlàbí Awọn kọmiti to n ṣe àyẹ̀wò awọn oludije du ipo gomina labẹ ẹgbẹ́ oselu APC ti ja igbakeji gomina tẹlẹ ni ipinle Osun, Alagba Iyiola Omisore ati awọn mẹfa miiran.Wọn ni iwe wọn ko pe lati dije du ipo gomina ipinlẹ naa. Awọn mẹfẹẹfa to ku naa ni – Babatunde Oralusi, Oyedotun Babayemi, Dr. Akin Ogunbiyi, Benedict Alabi, Adegoke Rasheed Okiki, ati Senator Babajide Omoworare.Iyiola Omisore ni awada Kẹri-Kẹri ni awọn kọmiti naa n se nitori ti wọn ...