Home / Art / Àṣà Oòduà / Omiyalé, àgbàrá ya sóòbù ní ìlú ilé-ifè.

Omiyalé, àgbàrá ya sóòbù ní ìlú ilé-ifè.

Ní òwúró ojó àíkú tí se èní,ojó kokàndínlógbòn osù keje odún 2018 ni òjò yí bèrè tí ó sì kò tí kò dáké di bíi agogo márùn-ún ìròlé.

Èyí fa kí àgbàrá ya wo ilé tí ó pò ní òpópónà Ede sí ifè, àti ònà tí a mò sí road 7, àti àwon ònà míràn, Ó tilè ti férè gba ilé míràn lówó onílé.

Tí ó bá je wípé ó ńkó wólo ni Ó sì dára, sùgbón kò wó lo bíkòse wípé ó dúró sí ojú kan tí kò sì lo, báwo ni àwon tí ó wà nínú ilé se ma jáde àti wípé báwo ni àwon tí ó wà ní ìta se ma w’olé?

Ìsèlè yí, nínú ìwádìí a gbó wípé èyí kó ni àkókò tí omi ma w’olé tí àgbàrá sì ma wo sóòbù ní ilé ifè ìlú tí ó wà ní ìpínlè Òsun ní orílè èdè Nìjíríà.
Kí ni ó le fa èyí? Sé ònà tí kò dára ni àbí àílè se ònà tí ó ye kí àgbàrá ma gba, èyí mà le poo, ní ìlú tí mùndùnmúdùn gbé ń sàn fún wàrà àti oyin, “èbè ni a be àwon ìjoba wa kí won bá wa mójú tó àwon ònà yí nítorí olórun” báyìí ni àwon ará ìlú ńké.

About Awoyemi Bamimore

One comment

  1. OLAMILEKAN

    Ko tiri, me man koru ye n’fe

VI

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

Omisore

Àwàdà kẹrí-Kẹrì ni àwọn kọmití tó ní mi ò lè díje du ipò gómìnà APC ni 2026 n ṣe – Omisore

Yínká Àlàbí Awọn kọmiti to n ṣe àyẹ̀wò awọn oludije du ipo gomina labẹ ẹgbẹ́ oselu APC ti ja igbakeji gomina tẹlẹ ni ipinle Osun, Alagba Iyiola Omisore ati awọn mẹfa miiran.Wọn ni iwe wọn ko pe lati dije du ipo gomina ipinlẹ naa. Awọn mẹfẹẹfa to ku naa ni – Babatunde Oralusi, Oyedotun Babayemi, Dr. Akin Ogunbiyi, Benedict Alabi, Adegoke Rasheed Okiki, ati Senator Babajide Omoworare.Iyiola Omisore ni awada Kẹri-Kẹri ni awọn kọmiti naa n se nitori ti wọn ...