Home / Art / Àṣà Oòduà / Ṣé Ìwọ mọ pé gbogbo agboolé nílùú Igbóọrà ní wọn ń bí ìbejì ?
ibeji

Ṣé Ìwọ mọ pé gbogbo agboolé nílùú Igbóọrà ní wọn ń bí ìbejì ?

Ṣé Ìwọ mọ pé gbogbo agboolé nílùú Igbóọrà ní wọn ń bí ìbejì ?

Fẹ́mi Akínṣọlá

Ṣé kò sí ìlú tí kò ní àdámọ́ ọ ti ẹ̀. Bẹ́ẹ̀ gẹ́lẹ́ lọ̀rọ̀ rí nílùú Igbóọrà .Igbóọrà jẹ́ ìlú kan tó kalẹ̀ si agbègbè Ìbàràpá nipinlẹ Ọyọ, tí ìgbàgbọ́ sì wà pé kò sí ile kan nínú ìlú náà tí wọn kò ti bí ìbejì ìbẹta tàbí ìbẹrin níbẹ̀.

Kódà, àwọn ọmọ bíbí ìlú àti àwọn a àjèjì tó bá ń gbé nínú ìlú, tó ń jẹ oúnjẹ wọn, tó sì ń mu omi wọn, ni okun ìbejì àbi ìbẹta wà nínú rẹ̀.
Ọdọọdún sì ni wọ́n máa ń ṣe ọdún ìbejì nílùú náà, èyí tó tun kò lọdun yii.
Ọ̀kan lara àwọn ọba alaye ìlú Igbóọrà, Ọba Adedamọla
Badmus, tíí ṣe Olu-Aso ti Ìbẹ̀rẹ̀kòdó sọ fáwọn oníròyìn pé, ìgbàgbọ́ wà pé ọbẹ̀ ìlasa àti àmàlà dúdú ló ń sokùnfà ìbí púpọ̀ nílùú ọhun.

Gẹ́gẹ́ bí ọba Badmus ti wí, o ti to aadọta ọdun sẹyin ti ilu Igbóọrà ti gbajúmọ̀ nípa bíbí ìbejì àbi ìbẹta, ohun tó sì tun jẹ́ pàtàkì ni pé, wọn kìí fi ìbejì tọrọ owó nílùú Igbóọrà. Ìgbàgbọ́ wọn ni pé gbogbo ìdílé t’áwon ọmọ náà bá yà ni wọn má a ń kóríire ràn .

http://iroyinowuro.com.ng/2019/10/18/%e1%b9%a3e-iwo-mo-pe-gbogbo-agboole-niluu-igboora-ni-won-n-bi-ibeji/

About ayangalu

VI

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

Omisore

Àwàdà kẹrí-Kẹrì ni àwọn kọmití tó ní mi ò lè díje du ipò gómìnà APC ni 2026 n ṣe – Omisore

Yínká Àlàbí Awọn kọmiti to n ṣe àyẹ̀wò awọn oludije du ipo gomina labẹ ẹgbẹ́ oselu APC ti ja igbakeji gomina tẹlẹ ni ipinle Osun, Alagba Iyiola Omisore ati awọn mẹfa miiran.Wọn ni iwe wọn ko pe lati dije du ipo gomina ipinlẹ naa. Awọn mẹfẹẹfa to ku naa ni – Babatunde Oralusi, Oyedotun Babayemi, Dr. Akin Ogunbiyi, Benedict Alabi, Adegoke Rasheed Okiki, ati Senator Babajide Omoworare.Iyiola Omisore ni awada Kẹri-Kẹri ni awọn kọmiti naa n se nitori ti wọn ...