Home / Art / Àṣà Oòduà / Yorùbá dún

Yorùbá dún

Hà à à!!
Elédùmàrè ìgbà wo
l’ènìyàn yόò to bo nínú hílàhílo òde ayé yìí
nà? Ki baálé ilé jáde láti òwúrò kùtùkùtù àná kό sí ma b’ojú
wéhìn wo, Ǹjé irú ìwà béè daa??
Àmò sà à!! Èyí tà á se sikù,
Ohun owό mi ό to, ma fi gogo fà.
‘modé yìí bami gbe sééré o jare,
‘Sáré tete wá’
Ní í seku Agéége.
Ìràwé kì í dájó ilè kó sùnkè
Onísèépé kò ní í sùnko igi
Kàká kó sunko igi.
A si yè é sílè.
Èrò, bé e délé
E bá mi ki Akíntáyò
E pé, kó sáré tete wá pàdé è mi
Èmi Olámidé l’Ókè-Àró.
(O fi èyí lélè. Ó mú òmíràn. Ó n pofò sí i:)
Idin kò sùn.
Ìdin kò wo.
Eja nlá kì í rójúú gbé ‘bú
Alákàn kì í rójúú gbé’lè odò
Oba tí n lu àgbálùgèdè fOlófin
Kò gbodò sun, kò gbodo wo
Bí Akíntáyò kò bá ri
Èmi Olámidé nínú yàrá yìí
Kò gbodò sùn, kò gbodò wo.
(Ó fi òògùn èyí lélè. Ó tún mú òmíran tí ó jé ìpara, ó
n pofò síi:)
Eku-kéku kì í rùn kò borí asín
Èèrà-kéèrà kì í rùn kó borí ìkamùdù.
Igikígi kì í rùn kó borí ifon.
‘Sè-sè-sè’ ni tègà.
Ojó tíjìímèrè bà fojú kan Alápìn-ín-ni
Lòràn inúu rèé tán
Àfè kì í jé orúko méji.
Bí Akíntáyò yóò bá wí,
Kó wi pé, àfèmi Olámidé
Bí Ayìnla mi yóò bá wí
Kó wí pé, àfèmi Olámidé
Àfè kì í jórúko méji…..
Tό! Tό!! Tό!!!….
Gbogbo èyí ìyàwó ilé to n se’rú èyí, e yami l’étí yín ooo….
Ìwà búrukú o lόrúko méjì, ohun búrukú níí se, ìwo to n f’όgun
b’oko lo pò nínú ilé, ọ̀rẹ́ẹ̀ dákun dáàbò jáwó níbè, kìí sohun to
daa, b’oko o ya dindinrin, a si padà wa d’afofungbemu, Ǹjé
iwúri ni fún ìyàwó ilé todi baálé ‘lé lόjijì? E je ka se’ránti
atúnbòtan, ìwà taa ba hù sílè lόmo wa a de bá, béè kòsí èdá ti
yόò hu’wà ìkà t’Oba mi adake-dajo o ní sésan fún, ìwo ìyàwó
onísééré, se ìrántí atúnbòtan…. (Ààbò òrò)
A kú ojúmó ooo gbogbo omo Oòduà pọ́nbélé, Aaji’re bí??

About Awoyemi Bamimore

VI

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

Omisore

Àwàdà kẹrí-Kẹrì ni àwọn kọmití tó ní mi ò lè díje du ipò gómìnà APC ni 2026 n ṣe – Omisore

Yínká Àlàbí Awọn kọmiti to n ṣe àyẹ̀wò awọn oludije du ipo gomina labẹ ẹgbẹ́ oselu APC ti ja igbakeji gomina tẹlẹ ni ipinle Osun, Alagba Iyiola Omisore ati awọn mẹfa miiran.Wọn ni iwe wọn ko pe lati dije du ipo gomina ipinlẹ naa. Awọn mẹfẹẹfa to ku naa ni – Babatunde Oralusi, Oyedotun Babayemi, Dr. Akin Ogunbiyi, Benedict Alabi, Adegoke Rasheed Okiki, ati Senator Babajide Omoworare.Iyiola Omisore ni awada Kẹri-Kẹri ni awọn kọmiti naa n se nitori ti wọn ...