Home / Art / Àṣà Oòduà / ‪#‎Òmìnira‬
ominira

‪#‎Òmìnira‬

 

Òmìnira ṣe pàtàkì,
Òmìnira ṣe koko fún gbogbo ohun Òlódùmarè dá,
Bí ènìyàn bá nínú ìnira tàbí ìgbèkùn,
Tí ó wá rí ìtúsílẹ̀,
Àyípadà rere a dé,
Ìfọ̀kàbalẹ̀ á wà,
A bọ lọ́wọ́ ìdarí ọ̀gá,
A bọ nínú wàhálà ọ̀gá àti àwọn tí ó kó sódì,
A le gbèrò fúnra rẹ,
A ṣí le tẹ́lẹ̀ ìlànà tó fẹ́,
Lọ́kàn ara rẹ,
Yàtọ̀ sí gbà tó wà làbẹ́ ìtọ́ni amúnísìn,
Bó tilẹ̀ jẹ́ pé òmìnira dára,
Gbogbo ẹ̀dà lo fẹ́ràn ẹ,
Ṣùgbọ́n ọ̀pọ́ òmìnira,
Lò n yọrí sí omi ìnira,
Fáwọn to gb’mìnira,
Ẹ wo orílè èdè Nàìjíríà,
A lòmíràn òṣèlú,
Ṣùgbọ́n abẹ ààbò amúnísìn la wà nínú okòwò,
Bẹ́ẹ̀ náà ni nínú àṣà, nínú ètò ẹ̀kọ́,
Ètò òṣèlú táa láa ni òmìnira rẹ̀,
Ìlànà òṣèlú amúnísìn náà la tún si n tẹ́lẹ̀,
Kí ló ṣe àwa ènìyàn aláwò dúdú,
Ṣe a kò le ronú fúnra wa ni?
Ẹ jẹ ki gbogbo àwa ọmọ orílè èdè Nàìjíríà àti gbogbo orílẹ̀ aláwò dúdú náà já fún ètò wa lọ́wọ́ àwọn tí a fi ṣe olórí,
Ẹ jẹ́ ká bọ àjàgà àwọn funfun sílè,
Ká mohun tí ṣe tiwa ṣe,
Dúdú làṣà, dúdú lẹ̀sìn, dúdú létó òṣèlú kí àwọn amúnísìn tó dé,
Kí ló wá dé tesin wa fọmọ tí ẹ̀ sílè tí n pọnmọ olọmọ.

Mo rọ gbogbo ọmọ orílè èdè Nàìjíríà àti orílẹ̀ aláwò dúdú ti o kú kí a gba ara lọ́wọ́ amúnísìn kí òmíràn má bá di omi ìnira mo wa lọ́wọ́…..

‪#‎Èdùmàrè‬ jẹ́ kí àlàáfíà jọba ní gbogbo orilẹ̀ èdè aláwò dúdú, kí a le jọ lá gbéga papọ̀…..

Inú mi dùn pé ilé aláwò dúdú ni mo ti wá

‪#‎ìwọ‬ ń kọ?

http://edeyorubatiorewa.blogspot.co.uk/2016/08/ominira.html

About ayangalu

One comment

  1. Translation please…

VI

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

Omisore

Àwàdà kẹrí-Kẹrì ni àwọn kọmití tó ní mi ò lè díje du ipò gómìnà APC ni 2026 n ṣe – Omisore

Yínká Àlàbí Awọn kọmiti to n ṣe àyẹ̀wò awọn oludije du ipo gomina labẹ ẹgbẹ́ oselu APC ti ja igbakeji gomina tẹlẹ ni ipinle Osun, Alagba Iyiola Omisore ati awọn mẹfa miiran.Wọn ni iwe wọn ko pe lati dije du ipo gomina ipinlẹ naa. Awọn mẹfẹẹfa to ku naa ni – Babatunde Oralusi, Oyedotun Babayemi, Dr. Akin Ogunbiyi, Benedict Alabi, Adegoke Rasheed Okiki, ati Senator Babajide Omoworare.Iyiola Omisore ni awada Kẹri-Kẹri ni awọn kọmiti naa n se nitori ti wọn ...