Home / Art / Àṣà Oòduà / Ìròyìn Òrofó ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.

Ìròyìn Òrofó ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.

1 Ààrẹ Buhari yóò dé lónìí láti orílẹ̀ èdè China.

2 Ọ̀jọ̀gbọ́n Ọ̀ṣínbàjò gba àlejò àwọn ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tí wọn gbé igbá orókè nínú ìdíje ìmọ̀ ẹ̀rọ ìgbàlódé.

3 Àwọn oníròyìn ń fi ìròyìn burúkú bá ìjọba Buhari jẹ́ – Alákòóso

4 Àwọn olùdíje ipò àarẹ nínú ẹgbẹ́ PDP yóò yọnu si ẹni ti o ba gbégbá orókè.

5 Mo ní ọgbọ́n ìṣèlú ju Buhari lọ – Turaki

6 Ìdìbò Ọ̀ṣun : Falae sọ ìdí tí àwọn olùdìbò ṣe gbọ́dọ̀ dìbò fún ẹgbẹ́ SDP yàtọ̀ di ẹgbẹ́ APC.

7 Oshiomole bẹnu àtẹ́ lu bí àwọn ọlọ́páà ṣe lọ tú ilé alàgbà Clark.

8 Ilé iṣẹ́ ọlọ́páà yọ àwọn ọlọ́páà tí wọn tú ilé alàgbà Edwin Clark.

9 Ilé iṣẹ́ ọlọ́páà gbé àwọn ẹni afurasí méjì-dín-lógún tí wọn dáná sun ilé iṣẹ́ ọlọ́páà ni ìlú Iwo lọ sí ilé ẹjọ́.

10 Ẹgbẹ́ APC ni Ìpínlẹ̀ Imo yóò lo ètò Ìdìbò gbangba-làṣá-ń-ta láti yan olùdíje gómìnà.

11 Àwọn olùdìbò mílíọ̀nù ó lè ní kò ì tíì wá gba káàdì Ìdìbò alálòpẹ́ ni Ìpínlẹ̀ Èkó – INEC.

12 Ẹgbẹ́ Ọdọ APC rọ àwọn ìgbìmọ́ kí wọn dín owó ìdíje kù.

13 Èrò bílíọ̀nù mẹ́rin ó lé ní bàálù gbé ní ọdún 2017 – IATA

14 Orílẹ̀ èdè India fọwọ́ sì kí ọkùnrin fẹ́ ọkùnrin gẹ́gẹ́ bí aya.

15 Orílẹ̀ èdè China yóò dá okoòwò tí ó lé ní tírílíọ̀nù méjì Náírà sí ilẹ̀ adúláwọ̀.

Ayé wa kò ní dàrú lágbára ELÉDÙMARÈ.. Àmín.

About Awoyemi Bamimore

VI

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

policeman

Ọ̀gbẹ́ni Olaoye déèdé pòórá nílé ìtura kan nílùú Akure

Fẹ́mi Akínṣọlá Ádùrá tí a máa ń ṣe ni pé kí á má rin àrin f’ẹsẹ̀sí.Mọ̀lẹ́bí ọkùnrin kan, Ògbẹ́ni Olaoye Olatunde, tó jẹ́ igbákejì ọ̀gá àgbà ilé ẹ̀kọ́ girama kan nílùú Ọwọ ti ké gbàjarè pé ọkùnrin náà di àwárítì lẹ́yìn tó lọ fún idanilẹkọ ní ilé ìtura Sunview nílùú Akure. Iyawo arakunrin naa salaye rẹ pe, ni ọjọ kẹrinlelogun oṣu Kẹjọ, ọdun 2025, ni ọkọ rẹ dagbere pe ohun n lọ fun idanilekọ kan n’iluu Akure, eyi ti wọn ...