Home / Art / Àṣà Oòduà / Ààrẹ Buhari ní ààbò wà fún ẹ̀mí ààrẹ́ àná, Goodluck Jonathan
gej

Ààrẹ Buhari ní ààbò wà fún ẹ̀mí ààrẹ́ àná, Goodluck Jonathan

Ààrẹ Buhari ní ààbò wà fún ẹ̀mí ààrẹ́ àná, Goodluck Jonathan

Ààrẹ Buhari ti pe Ààrẹ àná, Goodluck Jonathan lórí ẹ̀rọ ìbánisọ̀rọ̀,láti báa kẹ́dùn lórí ìkọlù àwọn agbébọn tó wáyé ní Òtuòkè tíí ṣe ìlú abínibí rẹ̀ nípìńlẹ̀ Bayelsa.

Nínú ọ̀rọ̀ orí fóònù náà, Ààrẹ Buhari kò fi bí ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣe ba òun nínú jẹ́ pamọ́. Ó ṣàkàwé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìṣẹ̀lẹ̀ ìbànújẹ́ ńlá tí ó sì kù díẹ̀ káátò.

Ààrẹ tún kan sárá sáwọn ṣọ́jà tó ń ṣọ́ Ilé Ààrẹ Jonathan fún bí wọ́n ṣe kojú ìjà náà gẹ́gẹ́ bí akin. Ó wá bá àwọn ẹbí ọmọ ogun tó ṣubú lójú ìjà náà dárò.

Ààrẹ Buhari wá fi dá àwọn ọmọ orílẹ̀èdè Nàìjíríà lójú pé àbò tó yẹ ń bẹ fún ẹ̀mí Ààrẹ àná náà àti gbogbo àwọn ọmọ orílẹ̀èdè Nàìjíríà láì yọ ẹni kan sílẹ̀ àti pé ààbò ni yóó túbọ̀ máa jẹ ìṣèjọba òun lógún.

Ni Ọjọ́ Ìṣẹ́gun ni ìròyìn jáde síta pé àwọn agbébọn kan kọlu ilu Otuoke tó jẹ́ ìlú Ààrẹ àná, Ọ Omọ̀wé Goodluck Jonathan tí wọ́n sì pa ṣọ́jà kan níbẹ̀.

Fẹ́mi Akínṣọlá

#iroyinowuro

About ayangalu

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED FOOL in Your ancestral Land.

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED Harlequin in Your ancestral Land.

The quote for today is a page from Toyin Falola’s book, ‘Yoruba Warlords of the 19th Century’. To a lot of Yoruba Muslims. Islam means servitude to Usman Dan Fodio’s estate at Sokoto. They indulge in the same idiocy that led to the fall of the great Hausa civilization. Many Yoruba Muslims from Oyo are a dangerously brainwashed set of people that would pose future danger for the preservation of Yorubaland like their ancestors who pledged allegiance to Ilorin and ...