Home / Art / Àṣà Oòduà / KÍ LÓ BÀJẸ́ LÉDÈ WA

KÍ LÓ BÀJẸ́ LÉDÈ WA

Ẹ jẹ́ kí a tibi pẹlẹbẹ mú ọ̀lẹ̀lẹ̀ jẹ.
N jẹ́ fífi gẹ̀ẹ́sì kọ́ni lédè Yorùbá le múni yege dáada nínú ẹ̀kọ́ èdè Yorùbá bí?
Gẹ́gẹ́ bíi òwe gẹ̀ẹ́sì kan tí ó wí pé, “the best way to understand a language is by speaking it”
Ọ̀NA KAN GBÒÓGÌ TÍ A FI LE GBỌ́ ÈDÈ KAN NÁÀ NI KÍ Á MA SỌÓ.
bi ko ba jẹ bẹ̀, àwọn àbùjẹ-ǹ-jẹkù tí ń bẹ nínú èdè gẹ̀ẹ́sì yóò ran Yorùbá náà. Bíi àpẹẹrẹ
Ìró èdè gẹ̀ẹ́sì ju iye álúfábẹ̀ẹ̀tì tí ó ní lọ.
Álúfábẹ̀ẹ̀tì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ lè ní ìró kan soso nínú èdè gẹ̀ẹ́sì.
Oral English
yóò se àkóbá fún mímọ ìró èdè àti àmì ń lò nínú èdè Yorùbá.
Àwọn òfin gírámà èdè gẹ̀ẹ́sì yàtọ̀ gédéńgbé sí ti èdè Yorùbá.
Njẹ̀ bí a bá ń fi ìtọ̀ táńbà sé ìdí le mọ́ bí ?
Ìgbẹ́ ò ní tán nídìí.
Bí òórùn ìgbẹ́ bá kúrò lára ẹni, ìtọ̀ ń ḱọ?
Ẹni bá ní ànfànì láti gbọ́ èdè lárúbáwá ọ̀rọ̀ yí le yé wọn dáada.
Wàláì tàlàì a kò lè fi èdè míràn ḱọ́ Yorùbá ju èdè Yorùbá náà lọ.
Ẹ wo ilẹ̀ chaina, ilẹ̀ korea, àti àwọn ilè lárúbáwa, wọ́n kìí kọ̀ gẹ̀ẹ́sì médè wọn, ọ̀tọ̀ lórìn ni wọ́n fií ń se, bí gẹ̀ẹ́sì bá wù wọ́n gbó wọn yó sẹ̀sẹ̀ lọ kọ́ọ ni.
N jẹ́ bí ó bá jẹ́ àwọn ìwé kíkà ìmọ̀ tí ó kù wà ní kíkọ lédè Yorùbá ni, òkèlè Yorùbá kò bá dùn ní kòlọ́bẹ̀,
Bí a bá fi Yorùbá kọ́ ìmọ̀ ẹ̀rọ, kòní sí wàhálà lórí lílo àkọtó èdè.
Bí èdè Yorù̀bá bá yé wa dáada a ó mọ àgbékà ọ̀rọ̀, èsì tí ó tọ́ àti bí ọ̀rọ̀ se wúwo tó.
“Bí ẹyẹ bá se fò ni kí á s’ọ̀kò rẹ.̀”
Bí a bá ń sọ̀rọ̀ ẹ jẹ́ kí á làdí ẹ̀ wò, kí a má joyè eléǹpe àkọ́kọ́ tó ní igbá wúwo ju àwo lọ, n ò pé kí a máà kọ́ èdè gẹ̀ẹ́sì, sùgbọ́n ẹ jẹ́ kí á gbọ́lá fún èdè wa,
Ẹ fi tó onílé létí, ẹ sọ f’álejò kó mọ̀.

About Awoyemi Bamimore

VI

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

Omisore

Àwàdà kẹrí-Kẹrì ni àwọn kọmití tó ní mi ò lè díje du ipò gómìnà APC ni 2026 n ṣe – Omisore

Yínká Àlàbí Awọn kọmiti to n ṣe àyẹ̀wò awọn oludije du ipo gomina labẹ ẹgbẹ́ oselu APC ti ja igbakeji gomina tẹlẹ ni ipinle Osun, Alagba Iyiola Omisore ati awọn mẹfa miiran.Wọn ni iwe wọn ko pe lati dije du ipo gomina ipinlẹ naa. Awọn mẹfẹẹfa to ku naa ni – Babatunde Oralusi, Oyedotun Babayemi, Dr. Akin Ogunbiyi, Benedict Alabi, Adegoke Rasheed Okiki, ati Senator Babajide Omoworare.Iyiola Omisore ni awada Kẹri-Kẹri ni awọn kọmiti naa n se nitori ti wọn ...