Home / Art / Àṣà Oòduà / Ènìyàn 148 míràn lárùn Covid-19 ní Nàìjíríà–Àjọ NCDC
Covid19

Ènìyàn 148 míràn lárùn Covid-19 ní Nàìjíríà–Àjọ NCDC

Ènìyàn 148 míràn lárùn Covid-19 ní Nàìjíríà–Àjọ NCDC

Ó ti pé ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àti márùndínládọ́jọ èèyan tó ti ní àrùn apinni léèmí yìí ní Nàìjíríà. Ìpínlẹ̀ Èkó ló ṣì ń léwájú.
Ní bí a ṣe ń kó ìròyìn yìí jọ. Iye àwọn tí àyẹwò ti fihàn pé wọ́n lárùn apinni léèmí coronavirus lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà ti tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ó dín àádọ́ta èèyàn báyìí.

Àjọ NCDC ló ṣàlàyé ẹ̀kúnrẹ́tẹ́ èyí nínú ìkéde alálàálẹ̀ tí wọ́n máa ń ṣe láti sọ ibi tí iṣẹ́ dé dúró lórí ọ̀rọ̀ àjàkálẹ̀ àrùn apinni léèmí Kofi 19 lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà.

Ìpínlẹ̀ Èkó ló ń léwájú lókè téńté àtẹ. Àwọn onímọ ètò ìlera kò sawun òótọ́ ọ̀rọ̀ náà pé, ó ṣeéṣe kó jẹ́ pé nítorí pé ìpínlẹ̀ Èkó ni ètò àyẹ̀wò rẹ̀ pọ̀jù lọ, ló fa èyí, bákan náà ni Ìpínlẹ Kano náà ti gòkè tẹ̀le pẹ̀lú ìbẹ̀rẹ̀ ètò àyẹ̀wò níbẹ̀ lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ awuyewuye tó wọ tọ ikú ọ̀wọọwọ̀ọ́ àti àìsí ìtọ́jú àti amójútó tó péye fún àjàkálẹ̀ àrùn ajániláyà pàtì méèmí ẹni lọ ọ̀hún tó mú ibùdó síbẹ̀ .

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED FOOL in Your ancestral Land.

History 101: What it takes to be a MENTALLY ENSLAVED Harlequin in Your ancestral Land.

The quote for today is a page from Toyin Falola’s book, ‘Yoruba Warlords of the 19th Century’. To a lot of Yoruba Muslims. Islam means servitude to Usman Dan Fodio’s estate at Sokoto. They indulge in the same idiocy that led to the fall of the great Hausa civilization. Many Yoruba Muslims from Oyo are a dangerously brainwashed set of people that would pose future danger for the preservation of Yorubaland like their ancestors who pledged allegiance to Ilorin and ...