Home / News From Nigeria / Breaking News / Àwọn olùgbé ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun ya bo ibùdó ìdìbò láti gba oúnjẹ kòrónáfairọ̀ọ̀sì
Àwọn olùgbé ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun ya bo ibùdó ìdìbò láti gba oúnjẹ kòrónáfairọ̀ọ̀sì

Àwọn olùgbé ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun ya bo ibùdó ìdìbò láti gba oúnjẹ kòrónáfairọ̀ọ̀sì

Bí ń tí a mọ̀ ọ́ jẹ bá ti tán, kí n tí a kìí jẹ papà á ó má ṣàfira ní o ,bí àwọn àgbà se fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé, ebi kìí wọ nú, kọ́rọ̀ míì ó wọ̀ ọ́ .

Èyí ló mú bí àwọn olùgbé ìpínlẹ̀ Ọṣun ti lọ péjú sáwọn ibùdó ìdìbò kóówá wọn láti gba àwọn oúnjẹ ìrànwọ́, èyí tí Ìjọba ìpínlẹ̀ náà pinnu fúnwọn.

Ní ọjọ́ Ìṣẹ́gun ni Ìjọba ìpínlẹ̀ Ọṣun kéde pé àwọn ti tẹ́wọ́ gba àwọn ohun amáyérọrùn tí wọ́n bèèrè fún láti bomi rọ ìrora táráàlù leè má a fara kó nípaṣẹ̀ àṣẹ ìgbélé tí Ìjọba pa.

Ìjọba ìpínlẹ̀ náà kéde pé ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ó lé ogún àpò ìrẹsì ní wọ́n yóó pín káàkiri ibùdó ìdìbò ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ó lé mẹ́wàá tó wà káàkiri ìpínlẹ̀ náà. Eléyìí tó fihàn pé àpò ìrẹsì méjì méjì ni yóó kan ibùdó ìdìbò kọ̀ọ̀kan.

Kí agogo mẹ́jọ ààbọ̀ tó lù làwọn èèyàn ti péjú sáwọn ibùdó ìdìbò káàkiri ìlú Oṣogbo tó jẹ́ olú ìlú ìpínlẹ̀ náà.

Àwọn olùgbé ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun ya bo ibùdó ìdìbò láti gba oúnjẹ kòrónáfairọ̀ọ̀sì

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

VI

Viral Video

Support Ooduarere

SUPPORT OODUARERE
Scan QR code below to Donate Bitcoin to Ooduarere
Bitcoin address:
1FN2hvx5tGG7PisyzzDoypdX37TeWa9uwb
x

Check Also

Osun: Òrìsà Olómo (The Mother of Children)

Osun: Motherly Love Yesterday was the peak of the Osun Osogbo festival, and it felt overwhelming.  The exciting bubbles were there as well. This may not be far from the fact that Arugba OSUNBUNMI, who couldn’t carry the sacred calabash last year because of its weight of it confidently carried it this year or because I watched her practice the carrying of calabash because of the access I have over the years and have gotten more closely in the last ...